4. Ó ṣe aṣọ èjìká fún ẹ̀wù èfòdì náà, èyí tí ó so mọ igun rẹ̀ méjèèjì, nítorí kí ó lè so pọ̀.
5. Ọnà ìgbànú híhun rẹ̀ rí bí i ti rẹ̀ ó rí bákan náà pẹ̀lú ẹ̀wù èfòdì ó sì sé e pẹ̀lú wúrà, àti pẹ̀lú aṣọ aláró, elésèé àlùkò, òdòdó àti pẹ̀lú ọ̀gbọ̀ olókùn dáradára, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pà sẹ fún Mósè.
6. Ó ṣìṣe òkúta óníkísì tí a tò sí ojú ìdè wúrà, tí a sì fín wọn gẹ́gẹ́ bí èdìdì pẹ̀lú orúkọ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì.
7. Ó sì so wọ́n mọ́ asọ èjìká ẹ̀wù èfòdì náà bí òkúta ìrántí fún àwọn ọmọ Isirẹli, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pà sẹ fún Mósè.
8. Ó ṣe iṣẹ́ ọnà sí igbáyà náà iṣẹ́ ọgbọ́n ọlọ́nà. Ó ṣe é bí, ẹ̀wù èfòdì: ti wúrà ti aṣọ aláró, ti elésèé àlùkò, ti òdòdó àti ti ọ̀gbọ̀ olókùn dáradára.