Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ékísódù 39:15-31 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Fún igbáyà náà, wọ́n ṣe ẹ̀wọ̀n iṣẹ́ kìkì wúrà, gẹ́gẹ́ bi okùn.

16. Wọ́n sì ṣe ojú ìdè wúrà méjì àti òrùka wúrà méjì, wọ́n sì so àwọn òkúta náà mọ́ igun méjèèjì igbáàyà náà.

17. Wọ́n sì so ẹ̀wọ̀n wúrà méjèèjì náà mọ́ àwọn òrùkà náà ni igun igbáàyà náà,

18. àti ní àwọn òpin ẹ̀wọ̀n tókù ni wọ́n fi mọ ojú ìdè méjèèjì, wọ́n so wọ́n mọ́ aṣọ èjìká ẹ̀wù èfòdì náà ní iwájú.

19. Wọ́n ṣe òrùka wúrà méjì, wọ́n sì so wọ́n mọ́ igun méjèèjì igbáyà náà ní etí tí ó wà ní inú lẹ́gbẹ̀ẹ́ ẹ̀wù èfòdì náà.

20. Wọ́n sì tún ṣe òrùka wúrà méjì sí i, wọ́n sì so wọ́n mọ́ ìdí aṣọ èjìká ní iwájú ẹ̀wù èfòdì náà tí ó sún mọ́ ibi tí a ṣe lọ́sọ̀ọ́ ní òkè ìgbànú ẹ̀wù èfòdí náà.

21. Wọn ṣo àwọn òrùka igbáàyà mọ́ àwọn òrùka ẹ̀wù èfòdì ọ̀já aṣọ aláró, kí a pa á pọ̀ mọ́ ìgbànú, nítorí kí igbáàyà náà má ṣe tú kúrò lára ẹ̀wù èfòdì náà gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mósè.

22. Ó sì ṣe ọ̀já àmùrè ẹ̀wù èfòdì gbogbo rẹ̀ jẹ́ aṣọ aláró iṣẹ́ alásọ híhun

23. Pẹ̀lú ihò ní àárin ọ̀já àmùrè náà gẹ́gẹ́ bí i ojú kọ́là, àti ìgbànú yí ihò yìí ká, nítorí kí ó má ba à ya.

24. Ó sì ṣe pomégíránátè ti aṣọ aláró, elésèé àlùkò, òdòdó àti ti ọ̀gbọ̀ olókùn dáradára yí ìsẹ́tí ọ̀já àmùrè náà ká.

25. Ó sì ṣe ago kìkì wúrà, ó sì ṣo wọ́n mọ́ àyìká ìsẹ́tí àárin pomégíránátè náà.

26. Aago àti pomégíránátè kọjú sí àyíká ìsẹ́ti ọ̀já àmùrè láti máa wọ̀ ọ́ fún iṣẹ́ àlùfáà, bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mósè.

27. Fún Árónì àti àwọn ọmọ rẹ, wọ́n ṣe àwọ̀tẹ́lẹ̀ ti ọ̀gbọ̀ dáradára tí iṣẹ́ alásọ híhun.

28. Àti fìlà ọ̀gbọ̀ dáradára, ìgbàrí ọ̀gbọ̀ àti aṣọ abẹ́ ọ̀gbọ̀ olókùn dáradára.

29. Ọ̀já náà jẹ́ ti ọ̀gbọ̀ olókùn dáradára, aṣọ aláró, elésèé àlùkò àti òdòdó iṣẹ́ alábẹ́rẹ́ bí Olúwa ṣe pàṣẹ fún Mósè.

30. Ó ṣe àwo, adé mímọ́, láti ara kìkì wúrà, wọ́n sì kọ̀wé sí i, gẹ́gẹ́ bí i ìkọ̀wé lórí èdìdì: “MÍMỌ́ SÍ Olúwa.”

31. Wọ́n sì so ọ̀já aláró mọ́ ọn láti ṣo ó mọ́ fìlà náà, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mósè.

Ka pipe ipin Ékísódù 39