Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ékísódù 39:15-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Fún igbáyà náà, wọ́n ṣe ẹ̀wọ̀n iṣẹ́ kìkì wúrà, gẹ́gẹ́ bi okùn.

16. Wọ́n sì ṣe ojú ìdè wúrà méjì àti òrùka wúrà méjì, wọ́n sì so àwọn òkúta náà mọ́ igun méjèèjì igbáàyà náà.

17. Wọ́n sì so ẹ̀wọ̀n wúrà méjèèjì náà mọ́ àwọn òrùkà náà ni igun igbáàyà náà,

18. àti ní àwọn òpin ẹ̀wọ̀n tókù ni wọ́n fi mọ ojú ìdè méjèèjì, wọ́n so wọ́n mọ́ aṣọ èjìká ẹ̀wù èfòdì náà ní iwájú.

19. Wọ́n ṣe òrùka wúrà méjì, wọ́n sì so wọ́n mọ́ igun méjèèjì igbáyà náà ní etí tí ó wà ní inú lẹ́gbẹ̀ẹ́ ẹ̀wù èfòdì náà.

20. Wọ́n sì tún ṣe òrùka wúrà méjì sí i, wọ́n sì so wọ́n mọ́ ìdí aṣọ èjìká ní iwájú ẹ̀wù èfòdì náà tí ó sún mọ́ ibi tí a ṣe lọ́sọ̀ọ́ ní òkè ìgbànú ẹ̀wù èfòdí náà.

21. Wọn ṣo àwọn òrùka igbáàyà mọ́ àwọn òrùka ẹ̀wù èfòdì ọ̀já aṣọ aláró, kí a pa á pọ̀ mọ́ ìgbànú, nítorí kí igbáàyà náà má ṣe tú kúrò lára ẹ̀wù èfòdì náà gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mósè.

22. Ó sì ṣe ọ̀já àmùrè ẹ̀wù èfòdì gbogbo rẹ̀ jẹ́ aṣọ aláró iṣẹ́ alásọ híhun

Ka pipe ipin Ékísódù 39