Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ékísódù 39:1-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Nínú aṣọ aláró, ti elésèé àlùkò àti ti òdòdó ni wọ́n fi ṣe aṣọ híhun fún àwọn òsìsẹ́ ní ibi mímọ́. Ó sì tún dá aṣọ mímọ́ fún Árónì gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mósè.

2. Ó ṣe ẹ̀wù èfòdì wúrà, ti aṣọ aláró, ti elésèé àlùkò, ti òdòdó àti ti ọ̀gbọ̀ olókùn dáradára.

3. Ó sì lu wúrà náà di ewé fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́, ó sì tún gé e láti fi ṣe iṣẹ́ sí aṣọ aláró, ti elésèé àlùkò, ti òdòdó, àti sínú ọ̀gbọ̀ dáradára ni ti iṣẹ́ ọgbọ́n iṣẹ́ ọnà.

4. Ó ṣe aṣọ èjìká fún ẹ̀wù èfòdì náà, èyí tí ó so mọ igun rẹ̀ méjèèjì, nítorí kí ó lè so pọ̀.

5. Ọnà ìgbànú híhun rẹ̀ rí bí i ti rẹ̀ ó rí bákan náà pẹ̀lú ẹ̀wù èfòdì ó sì sé e pẹ̀lú wúrà, àti pẹ̀lú aṣọ aláró, elésèé àlùkò, òdòdó àti pẹ̀lú ọ̀gbọ̀ olókùn dáradára, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pà sẹ fún Mósè.

6. Ó ṣìṣe òkúta óníkísì tí a tò sí ojú ìdè wúrà, tí a sì fín wọn gẹ́gẹ́ bí èdìdì pẹ̀lú orúkọ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì.

7. Ó sì so wọ́n mọ́ asọ èjìká ẹ̀wù èfòdì náà bí òkúta ìrántí fún àwọn ọmọ Isirẹli, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pà sẹ fún Mósè.

8. Ó ṣe iṣẹ́ ọnà sí igbáyà náà iṣẹ́ ọgbọ́n ọlọ́nà. Ó ṣe é bí, ẹ̀wù èfòdì: ti wúrà ti aṣọ aláró, ti elésèé àlùkò, ti òdòdó àti ti ọ̀gbọ̀ olókùn dáradára.

Ka pipe ipin Ékísódù 39