Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ékísódù 39:1-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Nínú aṣọ aláró, ti elésèé àlùkò àti ti òdòdó ni wọ́n fi ṣe aṣọ híhun fún àwọn òsìsẹ́ ní ibi mímọ́. Ó sì tún dá aṣọ mímọ́ fún Árónì gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mósè.

2. Ó ṣe ẹ̀wù èfòdì wúrà, ti aṣọ aláró, ti elésèé àlùkò, ti òdòdó àti ti ọ̀gbọ̀ olókùn dáradára.

3. Ó sì lu wúrà náà di ewé fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́, ó sì tún gé e láti fi ṣe iṣẹ́ sí aṣọ aláró, ti elésèé àlùkò, ti òdòdó, àti sínú ọ̀gbọ̀ dáradára ni ti iṣẹ́ ọgbọ́n iṣẹ́ ọnà.

4. Ó ṣe aṣọ èjìká fún ẹ̀wù èfòdì náà, èyí tí ó so mọ igun rẹ̀ méjèèjì, nítorí kí ó lè so pọ̀.

5. Ọnà ìgbànú híhun rẹ̀ rí bí i ti rẹ̀ ó rí bákan náà pẹ̀lú ẹ̀wù èfòdì ó sì sé e pẹ̀lú wúrà, àti pẹ̀lú aṣọ aláró, elésèé àlùkò, òdòdó àti pẹ̀lú ọ̀gbọ̀ olókùn dáradára, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pà sẹ fún Mósè.

6. Ó ṣìṣe òkúta óníkísì tí a tò sí ojú ìdè wúrà, tí a sì fín wọn gẹ́gẹ́ bí èdìdì pẹ̀lú orúkọ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì.

7. Ó sì so wọ́n mọ́ asọ èjìká ẹ̀wù èfòdì náà bí òkúta ìrántí fún àwọn ọmọ Isirẹli, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pà sẹ fún Mósè.

8. Ó ṣe iṣẹ́ ọnà sí igbáyà náà iṣẹ́ ọgbọ́n ọlọ́nà. Ó ṣe é bí, ẹ̀wù èfòdì: ti wúrà ti aṣọ aláró, ti elésèé àlùkò, ti òdòdó àti ti ọ̀gbọ̀ olókùn dáradára.

9. Igun rẹ̀ mẹ́rẹ̀ẹ̀rin rẹ̀ ṣe déédé ìwọ̀n ṣẹ̀ǹtímítà méjìlélógún ni gígùn rẹ̀, fífẹ̀ rẹ̀ náà sì jẹ́ ìwọ̀n sẹ̀ǹtímítà méjìlélógún ó sì jẹ́ ìsẹ́po méjì.

10. Ó sì to ìpele òkúta mẹ́rin oníyebíye sí i. Ní ipele kìn-in-ní ní rúbì wà, tapásì àti bérílù;

Ka pipe ipin Ékísódù 39