Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ékísódù 36:16-33 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

16. Wọ́n so àsọ títa márùn-ún pọ̀ mọ́ ara wọn, wọ́n sì tún so mẹ́fà tó kù mọ́ ara wọn.

17. Wọ́n sì pa àádọ́ta (50) ajábó sí ìsẹ́tí ìkángun aṣọ títa ní apá kan, wọ́n sì tún pa ajábó mìíràn sí ìsẹ́tí ìkángun aṣọ títa ní apá ibòmíràn.

18. Wọ́n ṣe àádọ́ta (50) ìkọ́ idẹ láti so Àgọ́ náà pọ̀ kí o lè jẹ́ ọ̀kan.

19. Wọ́n sì ṣe ìbòrí àwọ àgbò tí a rì ní pupa, àti ìbòrí màlúù odò lórí rẹ̀.

20. Wọ́n ṣe pákó igi kaṣíá tí ó dúró fún Àgọ́ náà.

21. Ọ̀kọ̀ọ̀kan pákó náà jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́wàá ní gíga àti ìgbọ̀nwọ́ kan ààbọ̀ ní fífẹ̀,

22. pẹ̀lú ìtẹ̀bọ̀ méjì tí ó kọjú sí ara wọn. Wọ́n ṣe gbogbo pákó Àgọ́ náà bí èyí.

23. Wọn ṣe ogún pákó sí ìhà gúsù Àgọ́ náà.

24. Wọ́n sì ṣe ogójì (40) fàdákà ihò ìtẹ̀bọ̀ lọ sí ìṣàlẹ̀ wọn ìtẹ̀bọ̀ méjì fún pákó kọ̀ọ̀kan, ọ̀kọ̀ọ̀kan ní ìṣàlẹ̀ ìtẹ̀bọ̀.

25. Fún ìhà kejì, ìhà àríwá Àgọ́ náà, wọ́n ṣe ogún pákó

26. ogójì (40) fàdákà ihò ìtẹ̀bọ̀ méjì ní ìṣàlẹ̀ pákó kọ̀ọ̀kan.

27. Wọ́n ṣe pákó mẹ́fà sì ìkángun, ní ìkangun ìhà ìwọ̀ oòrùn Àgọ́ náà,

28. pákó méjì ni wọ́n ṣe sí igun Àgọ́ náà ní ìkangun.

29. Ní igun méjèèjì yìí, pákó méjì ni ó wà níbẹ láti ìdí dé orí rẹ̀ wọ́n sì kó wọ́n sí òrùka kan; méjèèjì rí bákan náà.

30. Wọ́n jẹ́ pákó mẹ́jọ àti fàdákà mẹ́rìn-lélógún ìhò ìtẹ̀bọ̀, méjì wà ní ìṣàlẹ̀ kọ̀ọ̀kan.

31. Wọ́n sì tún ṣe ọ̀pá igi kaṣíà: márùn ún fún pakó ní ìhà kọ̀ọ̀kan Àgọ́ náà,

32. márùn-ún fún àwọn tí ó wà ní ìhà kejì, márùn-ún fún pákó tí ó wà ní ìhà ìwọ̀ oòrùn ní ìkangun Àgọ́ náà.

33. Wọ́n sì ṣe ọ̀pá àárin tí yóò fi jáde láti ìkangun dé ìkangun ní àárin àwọn pákó náà.

Ka pipe ipin Ékísódù 36