Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ékísódù 36:11-26 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. Wọ́n sì pa ajábó aṣọ aláró ní etí aṣọ títa kan láti ìsẹ́tí rẹ̀ dé ibi òpin, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ní o ṣe sí ìhà etí ikangun aṣọ títa kejì ní ibi òpin èkejì.

12. Àádọ́ta (50) ajábó ní ó pa lára aṣọ títa kan, àti àádọ́ta ajábó ni ó sì lò pa ní etí aṣọ títa tí ó wà ní ọ̀kánkán ara wọn.

13. Wọ́n sì ṣe àádọ́ta ìkọ́ wúrà, ó sì lò wọ́n láti fi kọ́ méjì aṣọ títa papọ̀ bẹ́ẹ̀ Àgọ́ náà sì di ọ̀kan.

14. Wọ́n ṣe aṣọ títa ti irun ewúrẹ́ fún Àgọ́ náà lórí Àgọ́ náà mọ́kànlá ni gbogbo rẹ̀ papọ̀.

15. Gbogbo aṣọ títa mọ́kọ̀ọ̀kànlá náà jẹ́ ìwọ̀n kan ọgbọ̀n (30) ìgbọ̀nwọ́, ní gígá àti ìgbọ̀nwọ́ mẹ́rin ní fífẹ̀.

16. Wọ́n so àsọ títa márùn-ún pọ̀ mọ́ ara wọn, wọ́n sì tún so mẹ́fà tó kù mọ́ ara wọn.

17. Wọ́n sì pa àádọ́ta (50) ajábó sí ìsẹ́tí ìkángun aṣọ títa ní apá kan, wọ́n sì tún pa ajábó mìíràn sí ìsẹ́tí ìkángun aṣọ títa ní apá ibòmíràn.

18. Wọ́n ṣe àádọ́ta (50) ìkọ́ idẹ láti so Àgọ́ náà pọ̀ kí o lè jẹ́ ọ̀kan.

19. Wọ́n sì ṣe ìbòrí àwọ àgbò tí a rì ní pupa, àti ìbòrí màlúù odò lórí rẹ̀.

20. Wọ́n ṣe pákó igi kaṣíá tí ó dúró fún Àgọ́ náà.

21. Ọ̀kọ̀ọ̀kan pákó náà jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́wàá ní gíga àti ìgbọ̀nwọ́ kan ààbọ̀ ní fífẹ̀,

22. pẹ̀lú ìtẹ̀bọ̀ méjì tí ó kọjú sí ara wọn. Wọ́n ṣe gbogbo pákó Àgọ́ náà bí èyí.

23. Wọn ṣe ogún pákó sí ìhà gúsù Àgọ́ náà.

24. Wọ́n sì ṣe ogójì (40) fàdákà ihò ìtẹ̀bọ̀ lọ sí ìṣàlẹ̀ wọn ìtẹ̀bọ̀ méjì fún pákó kọ̀ọ̀kan, ọ̀kọ̀ọ̀kan ní ìṣàlẹ̀ ìtẹ̀bọ̀.

25. Fún ìhà kejì, ìhà àríwá Àgọ́ náà, wọ́n ṣe ogún pákó

26. ogójì (40) fàdákà ihò ìtẹ̀bọ̀ méjì ní ìṣàlẹ̀ pákó kọ̀ọ̀kan.

Ka pipe ipin Ékísódù 36