Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ékísódù 32:30-35 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

30. Ní ọjọ́ kejì Mósè sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ̀yin ti dá ẹ̀ṣẹ̀ tí ó pọ̀. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí èmi yóò gòkè lọ bá Olúwa; bóyá èmi lè se ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀ yín.”

31. Bẹ́ẹ̀ ni Mósè padà tọ Olúwa lọ, ó sì wí pé, “Yé, kí ni ẹ̀ṣẹ̀ ńlá tí àwọn ènìyàn ti dá yìí! Wọ́n ti ṣe òrìsà wúrà fún ara wọn.

32. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, jọ̀wọ́ dárí ẹ̀ṣẹ̀ wọn jìn wọ́n ṣùgbọ́n tí kò bá sì ṣe bẹ́ẹ̀, pa oruko mi rẹ́ kúrò nínú ìwé tí ìwọ ti kọ.”

33. Olúwa dá Mósè lóhùn pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá dẹ́ṣẹ̀ sí mi, èmi yóò pa á rẹ́ kúrò nínú ìwé mi.

34. Ǹjẹ́ nísinsin yìí lọ, máa darí àwọn ènìyàn yìí lọ sí ibi ti mo sọ, angẹ́lì mi yóò sì máa lọ ṣáájú yín. Ìgbà ń bọ̀ fún mi tì èmi yóò ṣe ìbẹ̀wò, èmi yóò fi yà jẹ wọ́n fún ẹ̀ṣẹ̀ wọn.”

35. Olúwa sì yọ àwọn ènìyàn náà lẹ́nu, pẹ̀lú arun nítorí ohun tí wọ́n se ni ti ẹgbọrọ màlúù tí Árónì ṣe.

Ka pipe ipin Ékísódù 32