1. Nígbà tí àwọn ènìyàn rí i pé Mósè pẹ́ kí ó tó sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè wá, wọn péjọ yí Árónì ká, wọ́n sì wí pé, “Wá, dá òrìṣà tí yóò máa ṣáájú wa fún wa. Bí ó ṣe ti Mósè tí ó mú wa jáde láti Éjíbítì wá, àwa kò mọ́ ohun tí ó ti sẹlẹ̀ sí i.”
2. Árónì dá wọn lóhùn pé, “Ẹ bọ́ òrùka wúrà tí ó wà ní etí àwọn ìyàwò yín, tí àwọn ọmọkùnrin yín, àti tí àwọn ọmọbìnrin yín, kí ẹ sì mú wọn wá sí ọ̀dọ̀ mi.”