Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ékísódù 31:1-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Olúwa wí fún Mósè pé,

2. “Wò ó, èmi ti yan Bésálélì ọmọ Úrì, ọmọ Húrì, ti ẹ̀yà Júdà,

3. Èmi sì ti fi ẹ̀mí Ọlọ́run kún-un pẹ̀lú ọgbọ́n, agbára àti ìmọ̀ ní gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.

4. Láti se aláràbarà iṣẹ́ ní wúrà, fàdákà àti idẹ,

5. láti gbẹ́ òkúta àti láti tò wọ́n, láti ṣiṣẹ́ ní igi, àti láti ṣiṣẹ́ ní gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.

6. Ṣíwájú sí i, èmi ti yan Óhólíábù ọmọ Áhúsámákì, ti ẹ̀yà Dánì, láti ràn án lọ́wọ́. Bákan náà, èmi ti fi ọgbọ́n fún gbogbo àwọn oníṣẹ́ ọnà láti ṣe ohun gbogbo tí mo paṣẹ fún ọ:

7. Àgọ́ àjọ náà, àpótí ẹ̀rín pẹ̀lú ìtẹ́ àánú tí ó wà lórí rẹ̀, àti gbogbo ohun èlò àgọ́ náà,

8. tábìlì àti ohun èlò rẹ̀, ọ̀pá fìtílà tí ó jẹ́ kìkì wúrà àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, pẹpẹ tùràrí,

9. pẹpẹ ẹbọ sísun àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, agbada pẹ̀lú ẹṣẹ̀ rẹ̀

10. àti aṣọ híhun pẹ̀lú, papọ̀ pẹ̀lú aṣọ mímọ́ fún Árónì àlùfáà àti aṣọ fún àwọn ọmọ rẹ̀ nígbà tí wọ́n bá ń ṣiṣẹ́ bí àlùfáà,

11. òróró ìtasórí àti tùràrí olóòórùn dídùn fún ibi mímọ́. Kí wọ́n se wọ́n gẹ́gẹ́ bí mo ṣe paṣẹ fún ọ.”

12. Olúwa wí fún Mósè pé,

Ka pipe ipin Ékísódù 31