Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ékísódù 30:4-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Ìwọ yóò sì ṣe òrùka wúrà méjì fún pẹpẹ náà níṣàlẹ̀ ìgbátí méjèèjì ní ọ̀kánkán ìhà rẹ̀—láti gbá àwọn òpó rẹ̀ mú, láti lè máa fí gbé e.

5. Ìwọ yóò sì ṣe òpó igi kaṣíà, ìwọ yóò sì bọ́ wọ́n pẹ̀lú wúrà.

6. Ìwọ yóò gbé pẹpẹ náà sí iwájú aṣọ títa, èyí tí ó wà níwájú àpótí ẹ̀rí níwájú ìtẹ́ àánú èyí tí ó wà lórí àpótí ẹ̀rí níbi ti èmi yóò ti máa bá ọ pàdé.

7. “Árónì yóò sì máa jó tùràrí dídùn lórí pẹpẹ náà ní àràárọ̀, nígbà tí ó tún àwọn fítìlá náà ṣe.

8. Òun yóò sì tún jó tùràrí nígbà tí ó bá tan fìtílà ní àṣálẹ̀, bẹ́ẹ̀ ní tùràrí yóò máa jó títí láé níwájú Olúwa fún àwọn ìran tó ni ń bọ̀.

9. Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ mú Àjèjì tùràrí wá sórí pẹpẹ yìí tàbí ẹbọ sísun kankan tàbí ọrẹ oúnjẹ, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin kò gbọdọ̀ da ẹbọ ohun mímu sórí rẹ̀.

10. Árónì yóò sì máa ṣe ètùtù sórí àwọn ìwo rẹ̀ lẹ́ẹ̀kan lọ́dún. Óun yóò sì máa ṣe ètùtù ọdọọdún yìí pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀ ẹbọ ètùtù fún ìran tó ń bọ̀. Mímọ́ jùlọ ni sí Olúwa.”

11. Nígbà náà ni Olúwa wí fún Mósè pé,

Ka pipe ipin Ékísódù 30