Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ékísódù 27:15-21 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Àti aṣọ títa ìgbọ̀nwọ́ mẹ́ẹ̀dógún ní gíga yóò wá ní ìhà kejì, pẹ̀lú òpó mẹ́ta àti ihò ìtẹ̀bọ̀ mẹ́ta.

16. “Àti fún ẹnu ọ̀nà àgbàlá náà, pèṣè aṣọ títa, mítà mẹ́sàn-án ní gíga, ti aláró, elésèé àlùkò, ti òdòdó, àti ti ọ̀gbọ̀ olókùn wíwẹ́ tí a fi iṣẹ́ abẹ́rẹ́ ṣe, pẹ̀lú òpó mẹ́rin àti ihò ìtẹ̀bọ̀ mẹ́rin.

17. Gbogbo òpó ti ó wà ní àyíká àgbàlá náà ni a ó fi fàdákà ṣo pọ̀ àti ìkọ́, àti ihò ìtẹ̀bọ̀ idẹ.

18. Àgbàlá náà yóò jẹ́ mítà mẹ́rìndìnláàdọ́ta (46 mítà) ni gíga àti mítà mẹ́talélógún (23 mítà) ní fífẹ̀, pẹ̀lú aṣọ títa ti ọ̀gbọ̀ olókùn mítà méjì ní gíga, àti pẹ̀lú ihò ìtẹ̀bọ̀ idẹ.

19. Gbogbo irú iṣẹ́ tí ó wà kí ó ṣe, papọ̀ pẹ̀lú gbogbo èèkàn àgọ́ náà àti fún tí àgbàlá náà, kí ó jẹ́ idẹ.

20. “Ìwọ yóò sì pàṣẹ fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, kí wọn kí ó mú òróró ólífì dáradára tí a gún fún ọ wá, fún ìmọ́lẹ̀, kí fìtílà lè máa tàn ṣíbẹ̀.

21. Ní àgọ́ àjọ, lẹ́yìn òde láìsí aṣọ ìsélé tí ó wá níwájú ẹ̀rí náà, Árónì àti òun àti àwọn ọmọ rẹ̀, ni yóò tọ́jú rẹ̀ lati alẹ́, títí di òwúrọ̀ níwájú Olúwa: yóò sì di ìlànà láéláé ni ìrandíran wọn lọ́dọ̀ àwọn ọmọ Isírẹ́lì.

Ka pipe ipin Ékísódù 27