Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ékísódù 26:2-7 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Gbogbo aṣọ títa náà ni kí ó jẹ́ déédé ìgbọ̀nwọ́ mèjídínlọ́gbọ̀n ní gígùn àti ìgbọ̀nwọ́ mẹ́rin ni fífẹ̀.

3. Asọ títa márùn ún ni kí o papọ̀ mọ́ ara wọn, kí o sì ṣe bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú márùn-ún tókù.

4. Ìwọ yóò siṣe ojábó aṣọ aláró sí aṣọ títọ́ kan láti ìsẹ́tí rẹ̀ wá nibi ìsopọ̀, àti bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni ìwọ yóò ṣe ni etí ìkangun aṣọ títa kejì, ni ibi ìsopọ̀ kejì.

5. Ṣe àádọ́ta (50) ọ̀jábó sí aṣọ títa kan, àádọ́ta ojábó (30) ni kí ó ṣe sí etí aṣọ títa ni ìbò mìíràn, pẹ̀lú ọ̀jábó ní ọ̀kánkán ara wọn.

6. Nígbà náà ṣe àádọ́ta (50) ìkọ́ yóòkù kí o sì lò wọ́n láti fi fa àwọn aṣọ títa náà papọ̀, nítorí náà àgọ́ náà yóò jẹ́ ọ̀kan.

7. “Ṣe aṣọ títa irun ewúrẹ́ láti fi ṣe ibò sórí àgọ́ náà—kí ó jẹ́ mọ́kànlá papọ̀.

Ka pipe ipin Ékísódù 26