Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Deutarónómì 5:8-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. “Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ ṣe ère fún ara yín ní ìrí ohunkóhun lọ́run tàbí ní ilẹ̀ ní ìṣàlẹ̀ níhìn-ín tàbí nínú omi ní ìṣàlẹ̀.

9. Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ foríbalẹ̀ láti sìn wọ́n. Torí pé èmi Olúwa Ọlọ́run yín Ọlọ́run owú ni mí, tí í fi ìyà ẹ̀ṣẹ̀ baba jẹ ọmọ títí dé ìran kẹ́ta àti ẹ̀kẹ́rin ní ti àwọn tí ó kórìíra mi.

10. Ṣùgbọ́n mo ń fí ìfẹ́ han ẹgbẹẹgbẹ̀rùn-ún ìran àwọn tí ó fẹ́ràn mi, tí ó sì ń pa òfin mi mọ́.

11. “Ẹ má ṣe ṣi orúkọ Olúwa Ọlọ́run yín lò, torí pé ẹnikẹ́ni tí o bá ṣi orúkọ rẹ̀ lò kì yóò lọ láìjẹ̀bi.

12. “Ẹ kíyèsí ọjọ́ ìsinmi láti pa á mọ́ bí Olúwa Ọlọ́run yín ti pàṣẹ fún un yín.

13. Ọjọ́ mẹ́fà ni kí ẹ fi ṣiṣẹ́, kí ẹ ṣe iṣẹ́ ẹ yín pátapáta

Ka pipe ipin Deutarónómì 5