Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Deutarónómì 3:3-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Ọlọ́run wa fi Ógù ọba Báṣánì àti àwọn jagunjagun rẹ̀ lé wa lọ́wọ́. A pa wọ́n run láìṣẹ́ku ẹnì kankan.

4. Ní ìgbà náà ní a gba gbogbo àwọn ìlú rẹ̀. Kò sí ọ̀kankan tí a kò gbà nínú àwọn ọgọta (60) ìlú tí wọ́n ní: Gbogbo agbégbé Ágóbù, lábẹ́ ìjọba Ógù ní Báṣánì.

5. Gbogbo ìlú wọ̀nyí ní a mọ odi gíga yíká pẹ̀lú àwọn ìlẹ̀kùn àti irin. Ọ̀pọ̀ àwọn ìlú kékèké tí a kò mọ odi yíká sì tún wà pẹ̀lú.

6. Gbogbo wọn ni a parun pátapáta gẹ́gẹ́ bí á ti ṣe sí Síhónì ọba Hésíbónì, tí a pa gbogbo ìlú wọn run pátapáta: tọkùnrin tobìnrin àti àwọn ọmọ wọn.

7. Ṣùgbọ́n a kó gbogbo ohun ọ̀ṣìn àti ìkógún àwọn ìlú wọn, fún ara wa.

8. Ní ìgbà náà ni a ti gba ilẹ̀ tí ó wà ní Jọ́dánì láti odò Ánónì, títí dé orí òkè Hámónì lọ́wọ́ àwọn ọba Ámórì méjèèjì wọ̀nyí.

9. (Àwọn ará Sídónì ń pe Hámónì ní Sírónì: Àwọn Ámórì sì ń pè é ní Sénírì)

10. Gbogbo àwọn ìlú tí o wà ní orí òkè olórí títẹ́ náà ni a gbà àti gbogbo Gílíádì, àti gbogbo Báṣánì, títí dé Ṣálékà, àti Édíréì, ìlú àwọn ọba Ógù ní ilẹ̀ Báṣánì.

11. (Ógù tí í ṣe ọba Báṣánì nìkan ni ó ṣẹ́kù nínú àwọn ará Ráfátì. Ibùsùn rẹ̀ ni a fi irin ṣe, ó sì gùn ju ẹsẹ̀ bàtà mẹ́tàlá lọ ní gígùn àti ẹsẹ̀ bàtà mẹ́fà ní ìbú. Èyí sì wà ní Rábà ti àwọn Ámórì.)

Ka pipe ipin Deutarónómì 3