Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Deutarónómì 28:44-57 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

44. Yóò yà ọ́, ṣùgbọ́n o kì yóò yà á, òun ni yóò jẹ́ orí, ìwọ yóò jẹ́ ìrù.

45. Gbogbo ègun yìí yóò wá sórí rẹ, wọn yóò lé ọ wọn yóò sì bá ọ títí tí ìwọ yóò fi parun, nítorí ìwọ kò gbọ́ràn sí Olúwa Ọlọ́run rẹ, ìwọ kò sì kíyèsí àṣẹ àti òfin tí ó fi fún ọ.

46. Wọn yóò jẹ́ àmì àti ìyanu fún ọ àti fún irú ọmọ rẹ títí láé.

47. Nítorí ìwọ kò sin Olúwa Ọlọ́run rẹ ní ayọ̀ àti inú dídùn ní àkókò àlàáfíà.

48. Nítorí náà nínú ebi àti òùngbẹ, nínú ìhòòhò àti àìní búburú, ìwọ yóò sin àwọn ọ̀ta à rẹ tí Olúwa rán sí ọ. Yóò sì fi àjàgà irin bọ̀ ọ́ ní ọrùn, títí yóò fi run ọ́.

49. Olúwa yóò mú àwọn orílẹ̀ èdè wá sí ọ láti ọ̀nà jínjìn, bí òpin ayé, bí idì ti ń bẹ́ láti orí òkè sílẹ̀, orílẹ̀ èdè tí ìwọ kò gbọ́ èdè wọn.

50. Orílẹ̀ èdè tí ó rorò tí kò ní ojúrere fún àgbà tàbí àánú fún ọmọdé.

51. Wọn yóò jẹ ohun ọ̀sìn rẹ run àti àwọn èṣo ilẹ̀ rẹ títí tí ìwọ yóò fi parun. Wọn kì yóò fi hóró irúgbìn kan fún ọ, wáìnì túntún tàbí òróró, tàbí agbo ẹran màlúù rẹ kankan tàbí ọ̀wọ́ ẹran àgùntàn rẹ títí ìwọ yóò fi run.

52. Wọn yóò gbógun ti gbogbo ìlú ù rẹ títí tí odi ìdáàbòbò gíga yẹn tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé yóò fi wó lulẹ̀. Wọn yóò gbógun ti gbogbo ìlú ù rẹ jákèjádò ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fún ọ.

53. Nítorí ìyà tí ọ̀ta à rẹ yóò fi jẹ ọ́ nígbà ìgbógun tì, ìwọ yóò jẹ, ẹran ara ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin tí Olúwa Ọlọ́run ti fi fún ọ.

54. Ènìyàn jẹ́jẹ́ àti onímọ̀ jùlọ kò ní ní àánú fún arákùnrin ara rẹ̀ tàbí ìyàwó tí ó fẹ́ràn tàbí àwọn ọmọ rẹ̀ tí o wà láàyè,

55. Bẹ́ẹ̀ ni kì yóò fún ẹnikẹ́ni nínú ẹran-ara àwọn ọmọ rẹ̀ tí ó ń jẹ, nítorí kò sí ohun kan tí ó kù sílẹ̀ fún un nínú ìdótì náà àti ìpọ́njú tí àwọn ọ̀ta yóò fi pọ́n ọ lójú ní ìlú u rẹ.

56. Obìnrin tí àwọ̀ rẹ̀ tutù nínú u yín, tí ó si ṣe ẹlẹgẹ́, tí kò jẹ́ dáṣà láti fi àtẹ́lẹṣẹ̀ ẹ rẹ̀ kan ilẹ̀ nítorí ìkẹ́ra àti ìwà ẹlẹgẹ́, ojú u rẹ̀ yóò korò sí ọkọ oókan àyà a rẹ̀, àti sí ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àti ọmọ rẹ̀ obìnrin

57. ọmọ tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ bí láti inú u rẹ̀ àti àwọn ọmọ tí ó ti bí. Nítorí ó fẹ́ láti jẹ wọ́n ní ìkọ̀kọ̀ nígbà ìgbógun tì àti ní ìgbà ìpọ́njú tí ọ̀ta rẹ yóò fi jẹ ọ́ nínú àwọn ìlú rẹ.

Ka pipe ipin Deutarónómì 28