Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Deutarónómì 14:9-26 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. Nínú gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ń gbé inú omi, ẹ lè jẹ èyíkéyí tí ó ní lẹbẹ àti ìpẹ́.

10. Ṣùgbọ́n èyíkéyí tí kò bá ní lẹbẹ àti ìpẹ́, ẹ má ṣe jẹ ẹ́, nítorí pé àìmọ́ ni wọ́n jẹ́ fún un yín.

11. Ẹ lè jẹ ẹyẹ tí ó bá mọ́.

12. Ṣùgbọ́n ìwọ̀nyí ní ẹ kò gbọdọ̀ jẹ: idì, igún, àkàlà,

13. onírúurú àṣá àti àṣá alátagbà,

14. onírúurú ẹyẹ ìwò,

15. ògòǹgò, òyo, pẹ́pẹ́yẹdò àti onírúurú àwòdì,

16. onírúurú òwìwí,

17. òwìwí-ọ̀dàn, idì-okùn, ẹyẹ-àkọ̀,

18. òòdẹ̀, onírúurú ẹyẹ odò mìíràn, atọ́ka àti àdán.

19. Àti gbogbo kòkòrò tí ń fò tí wọ́n ń kọ́wọ̀ọ́ rín jẹ́ aláìmọ́ fun un yín, ẹ má ṣe jẹ wọ́n.

20. Ṣùgbọ́n ẹ lè jẹ èyíkéyí ẹ̀dá abìyẹ́ tí ó bá mọ́.

21. Ẹ má ṣe jẹ ohun tí ó ti kú sílẹ̀. Ẹ lè fún àwọn àjèjì tí ń gbé ní èyíkéyí nínú ìlú yín. Òun lè jẹ ẹ́ tàbí kí ẹ tà á fún àwọn àjèjì. Ṣùgbọ́n ènìyàn mímọ́ fún Olúwa Ọlọ́run yín ni ẹ̀yin jẹ́.Má ṣe ṣe ewúrẹ́ nínú wàrà ìyá rẹ̀.

22. Ẹ rí i dájú pé ẹ̀ ń fi ìdá kan nínú mẹ́wàá nínú irè oko yín lọ́dọọdún pamọ́ sí apákan

23. Ẹ jẹ ìdámẹ́wàá, oúnjẹ yín, wáìnì tuntun, òróró, àti àkọ́bí àwọn màlúù yín àti ewúrẹ́ ẹ yín, níwájú Olúwa Ọlọ́run yín, ní ibi tí yóò yàn bí ibùgbé orúkọ rẹ̀. Kí ẹ lè kọ́ bí a ṣé ń bọlá fún Olúwa Ọlọ́run yín nígbà gbogbo.

24. Bí ibẹ̀ bá jìn tí Olúwa Ọlọ́run rẹ sì ti bùkún fún ọ, tí o kò sì le ru àwọn ìdámẹ́wàá rẹ (nítorí pé ibi tí Olúwa yóò yàn láti fi orúkọ rẹ̀ sí jìnnà jù).

25. Ẹ pààrọ̀ àwọn ìdámẹ́wàá yín sówó, ẹ mú owó náà lọ sí ibi tí Olúwa yóò yàn.

26. Fi owó náà ra ohunkóhun tí o bá fẹ́, màlúù, àgùntàn, wáìnì, tàbí ọtí líle, tàbí ohunkóhun tí o bá fẹ́. Kí ìwọ àti ìdílé rẹ sì jẹ ẹ́ níwájú Olúwa níbẹ̀ kí ẹ sì máa yọ̀.

Ka pipe ipin Deutarónómì 14