Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Dáníẹ́lì 2:45-47 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

45. Gẹ́gẹ́ bí o ṣe rí i pé a gé òkúta láti ara òkè, láì ti ọwọ́ ẹnikẹ́ni wá, òkúta èyí tí ó fọ́ irin, idẹ, amọ̀, fàdákà àti wúrà sí wẹ́wẹ́.“Ọlọ́run tí ó tóbi ti fi han ọba, ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ ní ọjọ́ iwájú. Òtítọ́ ni àlá náà, bẹ́ẹ̀ ni ìtúmọ̀ rẹ̀ ṣe é gbẹ́kẹ̀lé.”

46. Nígbà náà, ni Nebukadinésárì ọba dojúbolẹ̀ níwájú u Dáníẹ́lì ó sì fi orí balẹ̀ fún un, ó sì pàṣẹ pé kí wọn kí ó mu ọrẹ àti òórùn tùràrí fún Dáníẹ́lì

47. Ọba wí fún Dáníẹ́lì pé, “Dájúdájú Ọlọ́run rẹ ni Ọlọ́run àwọn ọlọ́run àti Olúwa àwọn ọba gbogbo àti olùfihàn àwọn àsírí, nítorí tí ìwọ lè fi àsírí yìí hàn.”

Ka pipe ipin Dáníẹ́lì 2