Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Dáníẹ́lì 2:10-21 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Àwọn awòràwọ̀ sì dá ọba lóhùn pé, “Kò sí ènìyàn kan ní ayé tí ó lè sọ nǹkan tí ọba béèrè! Kò sí ọba náà bí ó ti wù kí ó tóbi àti kí ó lágbára tó, tí í béèrè irú nǹkan bẹ́ẹ̀ lọ́wọ́ àwọn onídán tàbí aláfọ̀ṣẹ tàbí awòràwọ̀.

11. Nǹkan tí ọba béèrè yìí ṣòro púpọ̀. Kò sí ẹni tí ó lè fi han ọba à fi àwọn òrìṣà, tí wọn kì í gbé láàrin ènìyàn.”

12. Èyí mú kí ọba bínú, ó sì kanra, nítorí náà ó pàṣẹ kí a pa gbogbo àwọn amòye Bábílónì run.

13. Nítorí náà àṣẹ yìí jáde lọ wí pé kí a pa àwọn amòye, wọ́n ránṣẹ́ pe Dáníẹ́lì pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ láti pa wọ́n.

14. Nígbà tí Áríókù, olórí àwọn olùṣọ́ ọba, jáde láti lọ pa àwọn amòye Bábílónì, Dáníẹ́lì sọ̀rọ̀ fún un pẹ̀lú ọgbọ́n àti òye.

15. Ó béèrè lọ́wọ́ olórí àwọn olùṣọ́ ọba wí pé, “Èéṣe tí àṣẹ ọba fi yá kánkán bẹ́ẹ̀?” Áríókù sì ṣe àlàyé ọ̀rọ̀ náà fún Dáníẹ́lì.

16. Nígbà náà ni Dáníẹ́lì wọlé tọ ọba lọ, ó sì tọrọ kí ọba fún òun ní ààyè, òun yóò fi ìtumọ̀ àlá náà hàn fún ọba.

17. Nígbà náà ni Dáníẹ́lì padà lọ sí ilé e rẹ̀, ó sì sọ fún àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ Hananíáyà, Míṣáẹ́lì àti Ásáríyà.

18. Ó sọ fún wọn pé kí wọn bèèrè fún àánú Ọlọ́run ọ̀run nípa àsírí náà, kí ọba má ba à pa àwọn run pẹ̀lú àwọn amòye Bábílónì.

19. Ní òru, àsírí náà hàn sí Dáníẹ́lì ní ojú ìran. Nígbà náà ni Dáníẹ́lì fi ògo fún Ọlọ́run ọ̀run

20. Dáníẹ́lì wí pé:“Ọpẹ́ ni fún orúkọ Olúwa láé àti láéláé;tirẹ̀ ni ọgbọ́n àti agbára

21. Ó yí ìgbà àti àkókò padà;ó mú ọba jẹ, ó ń mú wọn kúrò.Ó fún àwọn amòye ní ọgbọ́nàti ìmọ̀ fún àwọn tí ó ní òye.

Ka pipe ipin Dáníẹ́lì 2