Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ámósì 3:4-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Ǹjẹ́ Kìnnìún yóò ha bú ramúramù nínú igbo,bí kò bá ní ohun ọdẹ?Ọmọ kìnnìún yóò ha ké jáde nínú ìhó rẹ̀bí kò bá rí ohun kan mú?

5. Ǹjẹ́ ẹyẹ ṣubú sínú okùn ọdẹ lórí ilẹ̀nígbà tí a kò dẹ okùn ọdẹ fún un?Okùn ọdẹ ha lè hù jáde lórí ilẹ̀nígbà tí kò sí ohun tí yóò mú?

6. Nígbà tí ìpè bá dún ní ìlú,àwọn ènìyàn kò ha bẹ̀rù?Tí ewu bá wú ìlúkò ha ṣe Olúwa ni ó fà á?

7. Nítòótọ́ Olúwa Ọlọ́run kò ṣe ohun kanláìfi èrò rẹ̀ hànsí àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ̀.

8. Kìnnìún ti bú ramúramùta ni kì yóò bẹ̀rù? Olúwa Ọlọ́run ti sọ̀rọ̀ta ni le ṣe àìsọtẹ́lẹ̀?

9. Ẹ kéde ní ààfin Áṣídódùàti ní ààfin ní ilẹ̀ Éjíbítì.“Ẹ kó ara yín jọ sí orí òkè ńlá Samáríà;Kí ẹ sì wo ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ńlá láàrin rẹ̀àti ìnílára láàrin àwọn ènìyàn rẹ.”

Ka pipe ipin Ámósì 3