Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 9:8-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Olúwa ti dojú iṣẹ́ kan kọ Jákọ́bù;Yóò sì wá sórí Ísírẹ́lì.

9. Gbogbo ènìyàn ni yóò sì mọ̀ ọ́n—Éfáímù àti gbogbo olùgbé Ṣamáríà—tí ó sọ pẹ̀lú ìgbéragaàti gààrù àyà pé.

10. Àwọn bíríkì ti wó lulẹ̀ṣùgbọ́n a ó tún un kọ́ pẹ̀lú òkúta dídán,a ti gé àwọn igi ọ̀pọ̀tọ́ lulẹ̀ṣùgbọ́n igi kédárì ní a ó fí dípò wọn.

11. Ṣùgbọ́n Olúwa fún àwọn ọ̀ta Réṣínì ní agbára láti dojúkọ wọ́nó sì ti rú àwọn ọ̀ta wọn ṣókè.

12. Àwọn Árámínì láti ìlà-oòrùnàti Fílístínì láti ìwọ̀ oòrùnwọ́n si fi gbogbo ẹnu jẹ́ Ìsirẹli runNí gbogbo èyí ìbínú un rẹ̀ kò yí kúròṢùgbọ́n ọwọ́ rẹ̀ nà jáde ṣíbẹ̀.

Ka pipe ipin Àìsáyà 9