Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 9:4-7 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Nítorí gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ tí a ṣẹ́gun Mídíánì,ìwọ ti fọ́ ọ túútúúúàjàgà ti ń pa wọ́n lẹ́rù,ọ̀pá tí ó dábùú èjìká wọn,ọ̀gọ aninilára wọn.

5. Gbogbo bàtà jagunjagun tí a ti lò lójú ogunàti gbogbo ẹ̀wù tí a yí nínú ẹ̀jẹ̀,ni yóò wà fún ìjóná,àti ohun èlò iná dídá.

6. Nítorí a bí ọmọ kan fún wa,a fi ọmọkùnrin kan fún wa,ìjọba yóò sì wà ní èjìkáa rẹ̀.A ó sì má a pè é ní: ÌyanuOlùdámọ̀ràn, Ọlọ́run AlágbáraBaba ayérayé, Ọmọ ọba aládé Àlàáfíà.

7. Ní ti ìgbòòrò Ìjọba rẹ̀ àti àlàáfíà rẹ̀ ni kì yóò ní ìpẹ̀kun.Yóò jọba lórí ìtẹ́ Dáfídìàti lórí ẹ̀kún un rẹ̀ gbogbo,nípa ìfìdímúlẹ̀ àti ìgbéró rẹ̀,pẹ̀lú òtítọ́ àti òdodoláti ìgbà náà lọ àti títí láéláé.Ìtara Olúwa àwọn ọmọ-ogunni yóò mú èyi ṣẹ.

Ka pipe ipin Àìsáyà 9