Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 8:7-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. fún ìdí èyí, Olúwa fẹ́ mú wá sóríi wọnagbára ìkún omi odòọba Ásíríà àti ògo rẹ̀yóò sì bo gbogbo àyasíi rẹ̀gbogbo bèbè di bíbò mọ́lẹ̀

8. yóò sì gbá rìẹrìẹ dé Júdà, a gba orí ẹ̀ lọ,yóò gba ibẹ̀ lọ yóò sì mú un dọ́run.Ìyẹ́ apá rẹ̀ tí ó nà yóò bo gbogbo ìbú ilẹ̀ náàÌwọ Ìmánúẹ́lì.

9. Ké ariwo ogun, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè, kí a sì fọ́ọ yín túútúúú,fetísílẹ̀, ẹ̀yin ilẹ̀ jínjìn réré.Ẹ palẹ̀mọ́ fún ogun, kí a sì fọ́ ọ túútúúú!

10. Ẹ hun ète yín, yóò di títúká.Ẹ gbérò ètò náà, ṣùgbọ́n kì yóò dúró,nítorí Ọlọ́run wà pẹ̀lúu wa.

11. Olúwa bá mi sọ̀rọ̀ pẹ̀lú ọwọ́ agbára rẹ̀ lórí mi pẹ̀lú ìkìlọ̀ fún mi pé, èmi kò gbọdọ̀ tẹ̀lé ọ̀nà àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Ó wí pé:

12. “Má ṣe pe éyí ní ọ̀tẹ̀ohun gbogbo tí àwọn ènìyàn wọ̀nyí bá pè ní ọ̀tẹ̀,má ṣe bẹ̀rù ohun tí wọ́n bá bẹ̀rù,má sì ṣe fòyà rẹ̀.

13. Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni Ẹni tí ìwọ yóò kà sí mímọ́,Òun ni kí o bẹ̀rùÒun ni kí àyà rẹ̀ fò ọ́,

14. Òun yóò sì jẹ́ ibi mímọ́ṣùgbọ́n fún ilé Ísírẹ́lì méjèèjì ni yóò jẹ́, òkúta tí í mú ni kọṣẹ̀àti àpáta tí ó mú wọn ṣubúàti fún àwọn ènìyàn Jérúsálẹ́mù ni yóò jẹ́ tàkúté àti ẹ̀bìtì.

Ka pipe ipin Àìsáyà 8