Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 65:13-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. Nítorí náà ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí nìyìí:“Àwọn ìránṣẹ́ mi yóò jẹun;ṣùgbọ́n ebi yóò máa pa ẹ̀yin,àwọn ìránṣẹ́ mi yóò mu,ṣùgbọ́n òrùngbẹ yóò máa gbẹ ẹ̀yin;àwọn ìránṣẹ́ mi yóò ṣe àjọyọ̀,ṣùgbọ́n a ó dójú ti ẹ̀yin.

14. Àwọn ìránṣẹ́ mi yóò kọrinláti inú ayọ̀ ọkàn wọn wá,ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò kígbe sókèláti inú ìrora ọkàn yínàti ìpohùnréré ní ìròbìnújẹ́ ọkàn.

15. Ẹ̀yin yóò fi orúkọ yín sílẹ̀fún àwọn àyànfẹ́ mi gẹ́gẹ́ bí ègún; Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò sì pa yín,ṣùgbọ́n fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ni òunyóò fún ní orúkọ mìíràn

16. Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbàdúrà ìbùkún ní ilẹ̀ náàyóò ṣe é nípaṣẹ̀ Ọlọ́run òtítọ́;Ẹni tí ó bá búra ní ilẹ̀ náàyóò búra nípaṣẹ̀ Ọlọ́run òtítọ́.Nítorí ìyọnu àtijọ́ yóò di ìgbàgbéyóò sì farasin kúrò lójú mi.

17. “Kíyèsí i, Èmi yóò dáàwọn ọ̀run tuntun àti ayé tuntunA kì yóò rántí ohun àtẹ̀yìnwá mọ́,tàbí kí wọn wá sí ọkàn.

18. Ṣùgbọ́n ẹ yọ̀ kí inú yín dùn títí láénínú ohun tí èmi yóò dá,nítorí èmi yóò dá Jérúsálẹ́mù láti jẹ́ ohun ìdùnnúàti àwọn ènìyàn rẹ̀, ohun ayọ̀.

Ka pipe ipin Àìsáyà 65