Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 63:9-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. Nínú un gbogbo ìpọ́njúu wọn, inú òun pẹ̀lú bàjẹ́àti ańgẹ́lì tí ó wà níwájú rẹ̀ gbà wọ́n là.Nínú Ìfẹ́ àti àánú rẹ̀, ó rà wọ́n padà;ó gbé wọn ṣókè ó sì pọ̀n wọ́nní gbogbo ọjọ́ ìgbà n nì.

10. Ṣíbẹ̀ṣíbẹ̀ wọ́n ṣọ̀tẹ̀wọ́n sì ba Ẹ̀mí Mímọ́ rẹ̀ nínú jẹ́.Bẹ́ẹ̀ ni ó yípadà ó sì di ọ̀ta wọnòun tìkálára rẹ̀ sì bá wọn jà.

11. Lẹ́yìn náà ni àwọn ènìyàn rẹ̀ rántí ọjọ́ ìgbà n nì,àwọn ọjọ́ Mósè àti àwọn ènìyàn rẹ̀níbo ni ẹni náà wà tí ó mú wọn la òkun já,pẹ̀lú olùṣọ́ àgùntàn agbo ẹran rẹ̀?Níbo ni ẹni náà wà tí ó ránẸ̀mí Mímọ́ rẹ̀ sáàrin wọn,

12. ta ni ó rán ògo apá ti agbára rẹ̀láti wà ní apá ọ̀tún Mósè,ta ni ó pín omi níyà níwájú wọn,láti gba òkìkí ayérayé fún ara rẹ̀,

13. ta ni ó ṣíwájú wọn la àwọn ọ̀gbun nì já?Gẹ́gẹ́ bí ẹṣin ni gbangba ìlú wọn tí kò sì kọṣẹ̀;

14. gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́ ẹran tí ó lọ sí pápá oko,a fún wọn ní ìsinmi láti ọwọ́ Ẹ̀mí Olúwa.Báyìí ni ẹ ṣe tọ́ àwọn ènìyàn yínláti fún ara yín ní orúkọ kan tí ó lógo.

15. Bojúwolẹ̀ láti ọ̀run kí o sì rí iláti ìtẹ́ ògo rẹ, mímọ́ àti ológo.Níbo ni ipá àti agbára rẹ wà?Ìwà jẹ́ẹ́jẹ́ẹ́ rẹ àti àánú rẹ ni atí mú kúrò níwájúu wa.

Ka pipe ipin Àìsáyà 63