Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 54:13-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. Gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin rẹ ni Olúwa yóò kọ́,àlàáfíà àwọn ọmọ rẹ yóò jẹ́ ńlá àti púpọ̀.

14. Ní òdodo ni a ó fi ìdí rẹ kalẹ̀Ìwà ipá yóò jìnnà sí ọo kò ní bẹ̀rù ohunkóhunÌpayà la ó mú kúrò pátapáta;kò ní súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ.

15. Bí ẹnikẹ́ni bá tilẹ̀ bá ọ jà, kò ní jẹ́ láti ọwọ́ọ̀ mi;ẹnikẹ́ni tí ó bá bá ọ jà ni yóò túúbá fún ọ.

16. “Kíyèsí i, Èmi ni ó dá alágbẹ̀dẹtí ń fẹ́ iná èédú di èjò-inátí ó sì ń mú ohun èlò wá tí ó bá iṣẹ́ rẹ mu.Èmi náà sì ni ẹni tí ó dá apanirun láti ṣe iṣẹ́ ibi;

17. Kò sí ohun ìjà tí a ṣe sí ọ tí yóò ṣe nǹkan,ìwọ yóò já ahọ́nkáhọ́n tó bá fẹ̀ṣùn kàn ọ́ kulẹ̀.Èyí ni ogún àwọn ìránṣẹ́ Olúwa,èyí sì ni ìdáláre wọn láti ọ̀dọ̀ mi,”ni Olúwa wí.

Ka pipe ipin Àìsáyà 54