Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 52:1-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Jí, jí, Ìwọ Ṣíhónì,wọ ara rẹ ní agbára.Gbé aṣọ ògo rẹ wọ̀,Ìwọ Jérúsálẹ́mù, ìlú mímọ́ n nì.Àwọn aláìkọlà àti aláìmọ́kì yóò wọ inú un rẹ mọ́.

2. Gbọn eruku rẹ kúrò;dìde ṣókè, kí o sì gúnwà, Ìwọ Jérúsálẹ́mù.Bọ́ ẹ̀wọ̀n tí ń bẹ lọ́rùn rẹ kúrò,Ìwọ ọ̀dọ́mọbìnrin ìgbékùn Ṣíhónì.

3. Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa wí;“Ọ̀fẹ́ ni a tà ọ́,láìsanwó ni a ó sì rà ọ́ padà.”

4. Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.“Ní ìgbà àkọ́kọ́ àwọn ènìyàn mi ṣọ̀kalẹ̀lọ sí Éjíbítì láti gbé;láìpẹ́ ni Áṣíríà pọ́n wọn lójú.

5. “Àti ní àkókò yìí, kí ni mo ní níbí?” ni Olúwa wí.“Nítorí a ti kó àwọn ènìyàn mi lọ lọ́fẹ̀ẹ́,àwọn tí ó sì ń jọba lé wọn fi wọ́n ṣẹlẹ́yà,”ni Olúwa wí.“Àti ní ọjọọjọ́orúkọ mi ni a ṣọ̀rọ̀ òdì sí nígbà gbogbo.

Ka pipe ipin Àìsáyà 52