Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 51:21-23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

21. Nítorí náà ẹ gbọ́ èyí, ẹ̀yin tí a ti ṣẹ́ níṣẹ̀ẹ́,tí ọtí ń pa, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún wáìnì

22. Ohun tí Olúwa yín Alágbára jùlọ wí nìyìí,Ọlọ́run rẹ, ẹni tí ó ń pa ènìyàn an rẹ̀ mọ́“Kíyèsí i, mo ti mú un kúrò ní ọwọ́ọ̀ rẹkọ́ọ̀bù tí ó mú ọ ta gbọ̀ngbọ̀nọ́n;láti inú kọ́ọ̀bù náà, ẹ̀kan ìbínú mi,ni ìwọ kì yóò mu mọ́.

23. Èmi yóò fi lé àwọn apọ́nnílójú rẹ lọ́wọ́,àwọn tí ó wí fún ọ pé,‘Dọ̀bálẹ̀, tó bẹ́ẹ̀ tí a ó fi máa rìn lóríì rẹ.’Ìwọ náà ṣe ẹ̀yìn rẹ gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀gẹ́gẹ́ bí òpópónà láti máa rìn lóríi rẹ̀.”

Ka pipe ipin Àìsáyà 51