Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 5:13-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. Nítorí náà àwọn ènìyàn mi yóòlọ sí ìgbèkùnnítorí òye kò sí fún wọn,ebi ni yóò pa àwọn bọ̀rọ̀kìnní wọn kú;ẹgbàágbèje wọn ni òrùgbẹyóò sì gbẹ.

14. Nítorí náà isà òkú ti ń dátọ́mì gidigidi,ó sì ti ya ẹnu rẹ̀ sílẹ̀ gbagada,nínú rẹ̀ ni àwọn gbajúmọ̀ àti mẹ̀kúnnù yóò sọ̀kalẹ̀ sípẹ̀lú ọlá àti ògo wọn.

15. Báyìí, ènìyàn yóò di ìrẹ̀sílẹ̀àti ọmọnìyàn ni a sọ di onírẹ̀lẹ̀ojú agbéraga ni a sì rẹ̀ sílẹ̀.

16. Ṣùgbọ́n Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni a ó gbéga nípa ẹ̀tọ́ rẹ̀,Ọlọ́run ẹni mímọ́ yóò sì fi ara rẹ̀ hàn ní mímọ́ nípa òdodo rẹ̀.

17. Nígbà náà ni àwọn àgùntàn yóò máa jẹ́ ko ní ibùgbé e wọn,àwọn ọ̀dọ́ àgùntàn yóò máa jẹ nínú ahoro àwọn ọlọ́rọ̀.

18. Ègbé ni fún àwọn tí ń fi okùn,àti àwọn tí o dàbí ẹni pé wọ́n ń fí okùn kẹ́kẹ́ ẹ̀sìn fa ìkà,

19. sí àwọn tí ó sọ pé, “Jẹ́ kí Ọlọ́run ṣe kíákíá,jẹ́ kí ó yára ṣiṣẹ́ rẹ̀ kí a lè ríi,jẹ́ kí ó súnmọ́ bíjẹ́ kí ètò ẹni mímọ́ Ísírẹ́lì kí ó dé,kí àwa kí ó le mọ̀ ọ́n.”

Ka pipe ipin Àìsáyà 5