Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 5:11-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. Ègbé ni fún àwọn tí wọ́n dìdení kùtùkùtù òwúrọ̀láti lépa ọtí líle,tí wọ́n sì mu ún títí alẹ́ fi lẹ́títí wọ́n fi gbinájẹ pẹ̀lú wáìnì.

12. Wọ́n ní hápù àti láà níbi àṣè wọn,tamborínìn òun fèrè àti wáìnì,ṣùgbọ́n wọn kò ka iṣẹ́ Olúwa sí,kò sí ìbọ̀wọ̀ fún iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀.

13. Nítorí náà àwọn ènìyàn mi yóòlọ sí ìgbèkùnnítorí òye kò sí fún wọn,ebi ni yóò pa àwọn bọ̀rọ̀kìnní wọn kú;ẹgbàágbèje wọn ni òrùgbẹyóò sì gbẹ.

14. Nítorí náà isà òkú ti ń dátọ́mì gidigidi,ó sì ti ya ẹnu rẹ̀ sílẹ̀ gbagada,nínú rẹ̀ ni àwọn gbajúmọ̀ àti mẹ̀kúnnù yóò sọ̀kalẹ̀ sípẹ̀lú ọlá àti ògo wọn.

15. Báyìí, ènìyàn yóò di ìrẹ̀sílẹ̀àti ọmọnìyàn ni a sọ di onírẹ̀lẹ̀ojú agbéraga ni a sì rẹ̀ sílẹ̀.

16. Ṣùgbọ́n Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni a ó gbéga nípa ẹ̀tọ́ rẹ̀,Ọlọ́run ẹni mímọ́ yóò sì fi ara rẹ̀ hàn ní mímọ́ nípa òdodo rẹ̀.

17. Nígbà náà ni àwọn àgùntàn yóò máa jẹ́ ko ní ibùgbé e wọn,àwọn ọ̀dọ́ àgùntàn yóò máa jẹ nínú ahoro àwọn ọlọ́rọ̀.

18. Ègbé ni fún àwọn tí ń fi okùn,àti àwọn tí o dàbí ẹni pé wọ́n ń fí okùn kẹ́kẹ́ ẹ̀sìn fa ìkà,

19. sí àwọn tí ó sọ pé, “Jẹ́ kí Ọlọ́run ṣe kíákíá,jẹ́ kí ó yára ṣiṣẹ́ rẹ̀ kí a lè ríi,jẹ́ kí ó súnmọ́ bíjẹ́ kí ètò ẹni mímọ́ Ísírẹ́lì kí ó dé,kí àwa kí ó le mọ̀ ọ́n.”

Ka pipe ipin Àìsáyà 5