Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 43:6-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Èmi yóò sọ fún àríwá pé, ‘Fi wọ́n sílẹ̀!’àti fún gúṣù, ‘Má ṣe dá wọn dúró.’Mú àwọn ọmọkùnrin mi láti ọ̀nà jínjìn wáàti àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin mi láti ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé—

7. ẹnikẹ́ni tí a ń pe orúkọ mi mọ́,tí mo dá fún ògo mi,tí mo mọ̀ àti tí mo ṣe.”

8. Sin àwọn tí ó ní ojú ṣùgbọ́n tí wọ́n fọ́jú jáde,tí wọ́n ní etí ṣùgbọ́n tí wọn dití.

9. Gbogbo orílẹ̀ èdè kóra wọn jọàwọn ènìyàn sì kóra wọn papọ̀.Ta ni nínú wọn tó sọ àṣọtẹ́lẹ̀ yìítí ó sì kéde fún wa àwọn nǹkan ti tẹ́lẹ̀?Jẹ́ kí wọ́n mú àwọn ẹlẹ́rìí wọn wọlé wáláti fi hàn pé wọ́n tọ̀nàtó bẹ́ẹ̀ tí àwọn mìíràn yóò gbọ́, tíwọn yóò sọ pé, “Òtítọ́ ni.”

10. “Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí mi,” ni Olúwa wí,“Àti ìránṣẹ́ mi tí èmi ti yàn,tó bẹ́ẹ̀ tí ẹ̀yin yóò fi mọ̀ àti tí ẹ̀yin ó fi gbà ḿi gbọ́tí yóò sì yé e yín pé èmi ni ẹni náà.Ṣáájú mi kò sí ọlọ́run tí a dá,tàbí a ó wa rí òmìíràn lẹ́yìn mi.

Ka pipe ipin Àìsáyà 43