Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 42:5-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run wíẸni tí ó dá àwọn ọ̀run tí ó sì tẹ́ wọ́n ṣóde,tí ó tẹ́ ilẹ̀ ayé àti ohun gbogbo tí ó jáde nínú un wọn,Ẹni tí ó fún àwọn ènìyàn rẹ̀ ní èémíàti ẹ̀mí fún gbogbo àwọn tí ń rìn nínú un rẹ̀:

6. “Èmi, Olúwa, ti pè ọ́ ní òdodo;Èmi yóò di ọwọ́ọ̀ rẹ mú.Èmi yóò pa ọ́ mọ́, n ó sì ṣe ọ́láti jẹ́ májẹ̀mú fún àwọn ènìyànàti ìmọ́lẹ̀ fún àwọn aláìkọlà

7. láti la àwọn ojú tí ó fọ́,láti tú àwọn òǹdè kúrò nínú túbúàti láti tú sílẹ̀ kúrò nínú ẹ̀wọ̀nàwọn tí ó jókòó nínú òkùnkùn.

8. “Èmi ni Olúwa; orúkọ mi nìyìí!Èmi kì yóò fi ògo mi fún ẹlòmìíràntàbí ìyìn mi fún ère-òrìṣà.

9. Kíyèsí i, àwọn nǹkan àtijọ́ ti wáyé,àti àwọn nǹkan tuntun ni mo ti wí pé;kí wọn tó hù jádemo ti kéde rẹ̀ fún ọ.”

10. Kọ orin titun sí Olúwaìyìn rẹ̀ láti òpin ilẹ̀ ayé wá,ẹ̀yin tí ó ṣọ̀kalẹ̀ lọ sínú òkun, àtiohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀ẹ̀yin erékùṣù, àti gbogbo àwọn tí ń gbé inú un wọn.

11. Jẹ́ kí ihà àti àwọn ìlúu rẹ̀ kí ó gbé ohùn wọn ṣókè;jẹ́ kí ibùdó ti àwọn igi kédárì ń gbé máa yọ̀.Jẹ́ kí àwọn ènìyàn Ṣẹ́là kọrin fún ayọ̀;jẹ́ kí wọn pariwo láti orí òkè.

12. Jẹ́ kí wọn fi ògo fún Olúwaàti kí wọn sì kéde ìyìn rẹ̀ ní erékùṣù.

Ka pipe ipin Àìsáyà 42