Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 42:1-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. “Ìránṣẹ́ mi nìyìí, ẹni tí mo gbéró,àyànfẹ́ mi nínú ẹni tí mo láyọ̀;Èmi yóò fi Ẹ̀mí mi sínú rẹ̀òun yóò sì mú ìdájọ́ wá sórí àwọn orílẹ̀ èdè.

2. Òun kì yóò pariwo tàbí kígbe ṣókè,tàbí kí ó gbóhùn rẹ̀ ṣókè ní òpópónà.

3. Koríko odò títẹ̀ kan ni òun kì yóò fọ́àti òwú-àtùpà tí ń jó tan an lọlòun kì yóò fẹ́ pa.Ní òdodo ni yóò mú ìdájọ́ wá;

4. Òun kì yóò kọsẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni kò ní rẹ̀wẹ̀sìtítí tí yóò fi fi ìdájọ́ mulẹ̀ ní ayé.Nínú òfin rẹ̀ ni àwọn erékùṣù yóò fi ìrètíi wọn sí.”

5. Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run wíẸni tí ó dá àwọn ọ̀run tí ó sì tẹ́ wọ́n ṣóde,tí ó tẹ́ ilẹ̀ ayé àti ohun gbogbo tí ó jáde nínú un wọn,Ẹni tí ó fún àwọn ènìyàn rẹ̀ ní èémíàti ẹ̀mí fún gbogbo àwọn tí ń rìn nínú un rẹ̀:

6. “Èmi, Olúwa, ti pè ọ́ ní òdodo;Èmi yóò di ọwọ́ọ̀ rẹ mú.Èmi yóò pa ọ́ mọ́, n ó sì ṣe ọ́láti jẹ́ májẹ̀mú fún àwọn ènìyànàti ìmọ́lẹ̀ fún àwọn aláìkọlà

7. láti la àwọn ojú tí ó fọ́,láti tú àwọn òǹdè kúrò nínú túbúàti láti tú sílẹ̀ kúrò nínú ẹ̀wọ̀nàwọn tí ó jókòó nínú òkùnkùn.

8. “Èmi ni Olúwa; orúkọ mi nìyìí!Èmi kì yóò fi ògo mi fún ẹlòmìíràntàbí ìyìn mi fún ère-òrìṣà.

Ka pipe ipin Àìsáyà 42