Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 41:26-29 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

26. Ta ni ó sọ èyí láti ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀,tí àwa kò bá fi mọ̀,tàbí ṣáájú àkókò, tí àwa kò bá fi wí pé,‘Òun sọ òtítọ́’?Ẹnikẹ́ni kò sọ nípa èyí,ẹnikẹ́ni kò sàṣọtẹ́lẹ̀ rẹ̀,ẹnikẹ́ni kò gbọ́ ọ̀rọ̀ kan láti ọ̀dọ̀ rẹ̀.

27. Èmi ni ẹni àkọ́kọ́ tí ó sọ fún Ṣíhóńì pé,‘Wò ó, àwọn nìyìí!’Mo fún Jérúsálẹ́mù ní ìránṣẹ́ ìhìn ayọ̀ kan.

28. Èmi wò, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan—kò sí ẹnìkan nínú wọn tí ó lè mú ìmọ̀ràn wá,kò sí ẹnìkan tí ó lè dáhùn nígbà tí mo bi wọ́n.

29. Kíyèsí i, irọ́ ni gbogbo wọn!Gbogbo ìṣe wọn já sí asán;àwọn ère wọn kò ṣé kò yà fúnafẹ́fẹ́ àti dàrúdàpọ̀.

Ka pipe ipin Àìsáyà 41