Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 41:1-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. “Ẹ dákẹ́ jẹ́ ẹ́ níwájúù mi ẹ̀yin erékùṣù!Jẹ́ kí àwọn orílẹ̀ èdè tún agbára wọn ṣe!Jẹ́ kí wọn wá ṣíwájú kí wọn sọ̀rọ̀:Jẹ́ kí a pàdé pọ̀ ní ibi ìdájọ́.

2. “Ta ni ó ti ru ẹnìkan ṣókè láti ìlà-oòrùn wá,tí ó pè é ní òdodo sí iṣẹ́ tirẹ̀?Ó gbé àwọn orílẹ̀ èdè lé e lọ́wọ́ó sì ṣẹ́gun àwọn ọba níwájúu rẹ̀.Ó sọ wọ́n di erùpẹ̀ pẹ̀lú idà rẹ̀,láti kù ú níyàngbò pẹ̀lú ọrun rẹ̀.

3. Ó ń lé pa wọn ó sì tẹ̀ṣíwájú láì farapa,ní ojú ọ̀nà tí ẹṣẹ̀ rẹ̀ kò rìn rí.

4. Ta ni ó ti ṣe èyí tí ó sì ti jẹ́ kí ó wáyé,tí ó ti pe ìran-ìran láti àtètèkọ́ṣe?Èmi Olúwa pẹ̀lú ẹnì kìn-ín-ní wọnàti ẹni tí ó gbẹ̀yìn, Èmi ni ẹni náà.”

5. Àwọn erékùsù ti rí i wọ́n bẹ̀rù;ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé wárìrì.Wọ́n súnmọ́tòsí wọ́n sì wá síwájú

Ka pipe ipin Àìsáyà 41