Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 37:32-35 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

32. Nítorí láti Jérúsálẹ́mù ni àwọn àṣẹ́kù yóò ti wá,àti láti òkè Ṣíhónì ni ikọ̀ àwọn tí ó sálà.Ìtara Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni yóò mú èyí ṣẹ.

33. “Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa wí nípa ọba Ásíríà:“Òun kì yóò wọ ìlú yìí wátàbí ta ẹyọ ọfà kan níhìn-ínÒun kì yóò wá síwájúu rẹ pẹ̀lú asàtàbí kí ó kó dágunró sílẹ̀ fún un.

34. Nípa ọ̀nà tí ó gbàwá náà ni yóò padà lọ;òun kì yóò wọ inú ìlú yìí,”ni Olúwa wí.

35. “Èmi yóò dáàbò bo ìlú yìí èmi ó sì gbàá là,nítorí mi àti nítoríì Dáfídì ìránṣẹ́ mi!”

Ka pipe ipin Àìsáyà 37