Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 37:25-31 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

25. Èmi ti gbẹ́ kàǹga ní ilẹ̀ àjèjìmo sì mu omi ní ibẹ̀,pẹ̀lú àtẹ́lẹṣẹ̀ miÈmi ti gbẹ́ gbogbo omi àwọn odò Éjíbítì.’

26. “Ṣé o kò tí ì gbọ́?Tipẹ́ tipẹ́ ni mo ti fìdíi rẹ̀ mulẹ̀.Láti ìgbà pípẹ́ ni mo ti ṣètò rẹ̀;ní àkókò yìí ni mo mú wá sí ìmúṣẹ,pé o ti sọ àwọn ìlú olódi diàkójọpọ̀ àwọn òkúta

27. Àwọn ènìyàn, tí agbára ti wọ̀ lẹ́wù,ni wọ́n banújẹ́ tí a sì dójútì.Wọ́n dàbí ohun ọ̀gbìn nínú pápá,gẹ́gẹ́ bí ọ̀jẹ̀lẹ̀ èhù tuntun,gẹ́gẹ́ bí i koríko tí ó ń hù lórí òrùlé,tí ó jóná kí ó tó dàgbà ṣókè.

28. “Ṣùgbọ́n mo mọ ibi tí o wààti ìgbà tí o wá tí o sì lọàti bí inú rẹ ṣe ru sími.

29. Nítorí pé inú rẹ ru símiàti nítorí pé oríkunkun rẹ tidé etíìgbọ́ mi,Èmi yóò fi ìwọ mi sí ọ ní imú,àti ìjẹ mi sí ọ lẹ́nu,èmi yóò sì jẹ́ kí o padàláti ọ̀nà tí o gbà wá.

30. “Èyí ni yóò ṣe àmì fún ọ Ìwọ Heṣekáyà:“Ní ọdún yìí, ìwọ yóò jẹ ohun tí ó hù fúnraà rẹ̀,àti ní ọdún kejì ohun tí ó jáde láti ara ìyẹn.Ṣùgbọ́n ní ọdún kẹta, ẹ gbìn kí ẹ sì kórè,ẹ gbin ọgbà àjàrà kí ẹ sì jẹ èṣo wọn.

31. Lẹ́ẹ̀kan sí i, àṣẹ́ku láti ilé Júdàyóò ta gbòǹgbò níṣàlẹ̀ yóò sì ṣo èṣo lókè.

Ka pipe ipin Àìsáyà 37