Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 37:24-28 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

24. Nípa àwọn oníṣẹ́ rẹìwọ ti mú àbùkù bá Olúwa.Ìwọ sì ti sọ wí pé‘pẹ̀lú àwọn kẹ̀kẹ́ ẹṣin miÈmi ti gun orí òkè ńlá ńlá,ibi gíga jùlọ ti Lébánónì.Èmi ti gé igi kédárì rẹ tí ó ga jùlọ lulẹ̀,àti àyànfẹ́ igi páínì.Èmi ti dé ibi rẹ̀ tí ó ga jùlọ,igbó rẹ̀ tí ó dára jùlọ.

25. Èmi ti gbẹ́ kàǹga ní ilẹ̀ àjèjìmo sì mu omi ní ibẹ̀,pẹ̀lú àtẹ́lẹṣẹ̀ miÈmi ti gbẹ́ gbogbo omi àwọn odò Éjíbítì.’

26. “Ṣé o kò tí ì gbọ́?Tipẹ́ tipẹ́ ni mo ti fìdíi rẹ̀ mulẹ̀.Láti ìgbà pípẹ́ ni mo ti ṣètò rẹ̀;ní àkókò yìí ni mo mú wá sí ìmúṣẹ,pé o ti sọ àwọn ìlú olódi diàkójọpọ̀ àwọn òkúta

27. Àwọn ènìyàn, tí agbára ti wọ̀ lẹ́wù,ni wọ́n banújẹ́ tí a sì dójútì.Wọ́n dàbí ohun ọ̀gbìn nínú pápá,gẹ́gẹ́ bí ọ̀jẹ̀lẹ̀ èhù tuntun,gẹ́gẹ́ bí i koríko tí ó ń hù lórí òrùlé,tí ó jóná kí ó tó dàgbà ṣókè.

28. “Ṣùgbọ́n mo mọ ibi tí o wààti ìgbà tí o wá tí o sì lọàti bí inú rẹ ṣe ru sími.

Ka pipe ipin Àìsáyà 37