Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 32:1-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Wòó, ọba kan yóò jẹ nínú òdodoàwọn olórí yóò máa ṣàkóso ní ìdájọ́.

2. Ẹnì kọ̀ọ̀kan yóò dàbí ìdáàbòbò lọ́wọ́ afẹ́fẹ́àti ààbò kúrò lọ́wọ́ ìjì,gẹ́gẹ́ bí odò omi nínú aṣálẹ̀àti òjìji àpáta ńlá ní ilẹ̀ òrùngbẹ.

3. Nígbà náà ni ojú àwọn tí ó rí kò ní pàdé mọ́,àti etí àwọn tí ó gbọ́ yóò tẹ́tí sílẹ̀.

4. Ọkàn àwọn oníwàdùwàdù ni yóò là tí yóò sì yè,àti ahọ́n tí ń kólòlò ni yóò là geerege.

5. A kò ní pe òmùgọ̀ ní bọ̀rọ̀kìnní mọ́tàbí kí a fi ọ̀wọ̀ tí ó ga jù fún mọ̀dàrú.

6. Nítorí òmùgọ̀ ṣọ̀rọ̀ òmùgọ̀,ọkàn rẹ̀ kún fún ìwà ibi:òun hùwà àìwà-bí-Ọlọ́runó sì ń tan àṣìṣe tí ó kan Olúwa kalẹ̀;ẹni ebi ń pa ló fi sílẹ̀ lófoàti fún àwọn tí òrùngbẹ ń gbẹni ó mú omi kúrò.

Ka pipe ipin Àìsáyà 32