Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 28:17-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

17. Èmi yóò fi ìdájọ́ ṣe okùn òṣùwọ̀nàti òdòdó òjé òṣùwọ̀n;yìnyín yóò gbá ààbò yín dànù àti irọ́,omi yóò sì kún bo gbogbo ibi tíẹ ń farapamọ́ sí mọ́lẹ̀.

18. Májẹ̀muu yín tí ẹ bá ikú dá ni a ó fagi lé;àdéhùn yín pẹ̀lú ibojì ni kì yóò dúró.Nígbà tí ìbínú gbígbóná náà bá fẹ́ kọjá,a ó ti ipa rẹ̀ lù yín bolẹ̀.

19. Nígbàkúùgbà tí ó bá ti wá niyóò máa gbé ọ lọ,ni àràárọ̀, ní ọ̀sán àti ní òru,ni yóò máa fẹ́ kọjá lọ.”Ìmòye ọ̀rọ̀ ìmọ̀ yìíyóò máa mú ìpayà ńlá wá.

20. Ibùsùn kúrújù fún ìnara lé lórí,ìbora kò fẹ̀ tó láti yí ara yín ká.

21. Olúwa yóò dìde sókè gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣení òkè Péráṣímùyóò ru ara rẹ̀ ṣókè gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣení àfonífojì Gíbíónì—láti ṣe iṣẹ́ rẹ̀, abàmì iṣẹ́ ẹ rẹ̀,yóò ṣe iṣẹ́ rẹ̀, àní àjèjì iṣẹ́ rẹ̀.

22. Ní ìsinsìn yìí ẹ dákẹ́ ẹlẹ́yà ṣíṣe,bí bẹ́ẹ̀ kọ́ ìdè e yín yóò le sí i; Olúwa, àní Olúwa àwọn-ogun ti sọ fún minípa àṣẹ ìparun ti ó ti pa lórí gbogbo ilẹ̀ náà.

Ka pipe ipin Àìsáyà 28