Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 27:1-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ní ọjọ́ náà, Olúwa yóò fi idà rẹ̀ jẹni níyàidà rẹ̀ amúbí-iná tí ó tóbi tí ó sì lágbáraLẹ́fíátanì ejò tí ń yọ̀ tẹ̀ẹ̀rẹ̀ n nì,Lẹ́fíátanì ejò tí ń lọ́ bìrìkìtì;Òun yóò sì pa ewèlè inú òkun náà.

2. Ní ọjọ́ náà“Kọrin nípa ọgbà-àjàrà eléso kan.

3. ÈMI Olúwa ń bojú tó o,Mo ń bomirin ín láti ìgbàdégbà.Mò ń sọ́ ọ tọ̀sán tòrukí ẹnikẹ́ni má ba à pa á lára.

4. Inú ò bí mi.Bí ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n bá dojú ìjà kọ mí!Èmi yóò dìde sí wọn ní ogun;Èmi yóò sì dáná ṣun gbogbo wọn.

5. Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, jẹ́ kí wọn wá sọ́dọ̀ mi fún ààbò;jẹ́ kí wọ́n wá àlàáfíà pẹ̀lúu mi,bẹ́ẹ̀ ni, jẹ́ kí wọn wá àlàáfíà pẹ̀lúu mi.”

6. Ní ọjọ́ iwájú Jákọ́bù yóò ta gbòǹgbò,Ísírẹ́lì yóò tanná yóò sì rudièṣo rẹ̀ yóò sì kún gbogbo ayé.

7. Ǹjẹ́ Olúwa ti lù úgẹ́gẹ́ bí ó ti lu àwọn tí ó lù ú bolẹ̀?Ǹjẹ́ a ti pa ágẹ́gẹ́ bí a ti pa àwọn tí ó pa á?

8. Nípa ogun-jíjà àti lílé nílùú ni ófi dojú kọ ọ́pẹ̀lú ìjì gbígbóná ni ó lé e jáde,gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ tí afẹ́fẹ́ ìlà oorùn fẹ́

Ka pipe ipin Àìsáyà 27