Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 24:4-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Ilẹ̀ ayé ti gbẹ ó sì ṣá,ayé ń ṣòjòjò, àárẹ̀ mú un,àwọn ẹni gíga ilẹ̀ ayé wà nínú ìpọ́njú

5. àwọn ènìyàn ayé ti bà á jẹ́;wọ́n ti pa àwọn òfin runwọ́n ṣe lòdì sí àwọn ìlànàwọ́n sì ti ba májẹ̀mú ayérayé jẹ́.

6. Nítorí náà, ègún kan ti jẹ ayé run;àwọn ènìyàn rẹ̀ ní láti ru ẹ̀bi wọn.Nítorí náà, àwọn olùgbé ayé ti gbiná dànù,àwọn ẹ̀tàhóró ló sì kù.

7. Wáìnì tuntun ti gbẹ, àjàrà sì ti rọ,gbogbo àwọn alárìíyá sì kérora.

8. Àríyá ti tamborínì ti dákẹ́ariwo àwọn tí ń ṣàjọyọ̀ ti dáwọ́ dúróayọ̀ hápù ti dákẹ́ jẹ́ẹ́.

9. Kò ṣeéṣe fún wọn láti máa mu wáìnì pẹ̀lú orin kíkọ mọ́ọtí líle ti di ìkorò fún àwọn ọ̀mu.

10. Ìlú tí a run ti dahoro,ẹnu ọ̀nà à bá wọlé kọ̀ọ̀kan ni a dí pa.

Ka pipe ipin Àìsáyà 24