Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 24:20-23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

20. Ilẹ̀ ayé yí gbiri bí ọ̀mùtí,ó bì síwá ṣẹ́yìn bí ahéré nínú afẹ́fẹ́;Ẹ̀bi ìṣọ̀tẹ̀ rẹ̀ ń pa á lẹ́rùtó bẹ́ẹ̀ tí ó fi ṣubú láìní lè dìde mọ́.

21. Ní ọjọ́ náà ni Olúwa yóò jẹ ẹ́ níyàgbogbo agbára tí ó wà lókè lọ́runàti àwọn ọba tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé.

22. A ó dà wọ́n papọ̀gẹ́gẹ́ bí ẹlẹ́wọ̀n tí a dè nínú un túbú,a ó tì wọ́n mọ́ inú ẹ̀wọ̀na ó sì jẹ wọ́n ní ìyà lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́.

23. A ó rẹ òṣùpá sílẹ̀, ojú yóò sì ti òòrùn;nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò jọbaní orí òkè Ṣíhónì àti ní Jérúsálẹ́mù,àti níwájú àwọn alàgbà rẹ ní ògo.

Ka pipe ipin Àìsáyà 24