Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 24:16-23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

16. Láti òpin ayé wá ni a ti gbọ́ orin;“Ògo ni fún olódodo n nì.”Ṣùgbọ́n mo wí pé, “mo ṣègbé, mo ṣègbé!”“Ègbé ni fún mi!Alárékérekè dalẹ̀!Pẹ̀lú ìhàlẹ̀ ni àgàbàgebè fi dalẹ̀!”

17. Ìpáyà, isà-òkú, àti ìdẹkùn ń dúró dè ọ́,Ìwọ ènìyàn ilẹ̀ ayé.

18. Ẹnikẹ́ni tí ó bá sá nítorí ariwo ìpayàyóò ṣubú sínú ihò,ẹnikẹ́ni tí ó bá sì yọ́ jáde nínú ihòni ìdẹkùn yóò gbámú.Ibodè ọ̀run ti wà ní sísí sílẹ̀Ìpìlẹ̀ ayé mì tìtì.

19. Ilẹ̀ ayé ti fọ́ilẹ̀ ayé ti fọ́ dànù,a ti mi ilẹ̀ ayé rìrìrìrì.

20. Ilẹ̀ ayé yí gbiri bí ọ̀mùtí,ó bì síwá ṣẹ́yìn bí ahéré nínú afẹ́fẹ́;Ẹ̀bi ìṣọ̀tẹ̀ rẹ̀ ń pa á lẹ́rùtó bẹ́ẹ̀ tí ó fi ṣubú láìní lè dìde mọ́.

21. Ní ọjọ́ náà ni Olúwa yóò jẹ ẹ́ níyàgbogbo agbára tí ó wà lókè lọ́runàti àwọn ọba tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé.

22. A ó dà wọ́n papọ̀gẹ́gẹ́ bí ẹlẹ́wọ̀n tí a dè nínú un túbú,a ó tì wọ́n mọ́ inú ẹ̀wọ̀na ó sì jẹ wọ́n ní ìyà lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́.

23. A ó rẹ òṣùpá sílẹ̀, ojú yóò sì ti òòrùn;nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò jọbaní orí òkè Ṣíhónì àti ní Jérúsálẹ́mù,àti níwájú àwọn alàgbà rẹ ní ògo.

Ka pipe ipin Àìsáyà 24