10. Ìlú tí a run ti dahoro,ẹnu ọ̀nà à bá wọlé kọ̀ọ̀kan ni a dí pa.
11. Ní òpópónà ni wọ́n ti ń kígbe fún wáìnìgbogbo ayọ̀ọ wọn ti di ìbànújẹ́,gbogbo àríyá ni a lé kúrò lórí ilẹ̀ ayé.
12. Ìlú ni a ti fi sílẹ̀ ní ahoro,ìlẹ̀kùn rẹ̀ ni a sì ti pa bámú bámú.
13. Bẹ́ẹ̀ ni yóò sì rí ní orí ilẹ̀ ayéàti láàrin àwọn orílẹ̀ èdè pẹ̀lú,gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí a lu igi ólífì,tàbí gẹ́gẹ́ bí i pàǹtí tí ó ṣẹ́kù lẹ́yìntí a kórè èso tán.
14. Wọ́n gbé ohùn wọn ṣókè, wọ́n sì hó fún ayọ̀;láti ìwọ̀ oòrùn ni wọn yóò ti polongoọlá-ńlá Olúwa.
15. Nítorí náà ní ìlà oòrùn ẹ fi ògo fún Olúwa;gbé orúkọ Olúwa ga, àníỌlọ́run Ísírẹ́lì,ní àwọn erékùṣù ti inú òkun,
16. Láti òpin ayé wá ni a ti gbọ́ orin;“Ògo ni fún olódodo n nì.”Ṣùgbọ́n mo wí pé, “mo ṣègbé, mo ṣègbé!”“Ègbé ni fún mi!Alárékérekè dalẹ̀!Pẹ̀lú ìhàlẹ̀ ni àgàbàgebè fi dalẹ̀!”
17. Ìpáyà, isà-òkú, àti ìdẹkùn ń dúró dè ọ́,Ìwọ ènìyàn ilẹ̀ ayé.
18. Ẹnikẹ́ni tí ó bá sá nítorí ariwo ìpayàyóò ṣubú sínú ihò,ẹnikẹ́ni tí ó bá sì yọ́ jáde nínú ihòni ìdẹkùn yóò gbámú.Ibodè ọ̀run ti wà ní sísí sílẹ̀Ìpìlẹ̀ ayé mì tìtì.
19. Ilẹ̀ ayé ti fọ́ilẹ̀ ayé ti fọ́ dànù,a ti mi ilẹ̀ ayé rìrìrìrì.