Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 23:1-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ọ̀rọ̀ ìmọ̀ tí ó kan Tírè:Pohùnréré, ìwọ ọkọ̀-ojú omi Táṣíṣì!Nítorí a ti pa Tírè runláìsí ilé tàbí èbúté.Láti ilẹ̀ Ṣáípúrọ́sì niọ̀rọ̀ ti wá sọ́dọ̀ wọn.

2. Dákẹ́ jẹ́ẹ́, ẹ̀yin ènìyàn erékùṣùàti ẹ̀yin oníṣòwò ti Sídónì,ẹ̀yin tí àwọn awẹ̀kun ti sọ dọlọ́rọ̀.

3. Láti orí àwọn omi ńláni irúgbìn oníhóró ti ilẹ̀ Ṣíhórì ti wáìkóórè ti Náì ni owóòná Tírè,òun sì ti di ibùjókòó ọjà fúnàwọn orílẹ̀ èdè.

4. Kí ojú kí ó tì ọ́, ìwọ Ṣídónì àti ìwọàní ìwọ ilé-ààbò ti òkun,nítorí òkun ti sọ̀rọ̀:“Èmi kò tí ì wà ní ipò ìrọbí tàbí ìbímọ ríÈmi kò tí ì wọ àwọn ọmọkùnrintàbí kí n tọ́ àwọn ọmọbìnrin dàgbà rí.”

5. Nígbà tí ọ̀rọ̀ bá dé Éjíbítì,wọn yóò wà ní ìpayínkeke nípaìròyìn láti Tírè.

Ka pipe ipin Àìsáyà 23