Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 2:6-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Ìwọ ti kọ àwọn ènìyàn rẹ sílẹ̀,ìwọ ilé Jákọ́bù.Wọ́n kún fún ìgbàgbọ́ tí kò lẹ́sẹ̀ ńlẹ̀ tí ó ti ìlà oòrùn wá,wọ́n ń wo iṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí àwọn Fílístínìwọ́n ń pa ọwọ́ pọ̀ pẹ̀lú àwọn abọ̀rìṣà

7. Ilẹ̀ wọ́n kún fún fàdákà àti wúràìṣúra wọn kò sì ní òpin.Ilẹ̀ ẹ wọn kún fún ẹṣin,kẹ̀kẹ́ ogun wọn kò sì lópin.

8. Ilẹ̀ ẹ wọn kún fún ère,wọ́n sì ń foríbalẹ̀ fún iṣẹ́ọwọ́ ara wọn,èyí tí ìka ọwọ́ àwọn tikálára wọn ti ṣe.

9. Nítorí náà ni a ó ṣe rẹ ènìyàn sílẹ̀ìran ọmọ ènìyàn ni yóò sì di onírẹ̀lẹ̀,má ṣe dáríjìn wọ́n.

10. Wọ inú àpáta lọ,fi ara pamọ́ nínú èrùpẹkúrò nínú ìpayà Olúwa,àti ògo ọlá ńlá rẹ̀!

11. Ojú agbéraga ènìyàn ni a ó rẹ̀ sílẹ̀a ó sì tẹrí ìgbéraga ènìyàn ba, Olúwa nìkan ṣoṣo ni a ó gbéga ní ọjọ́ náà.

12. Olúwa àwọn ọmọ-ogun ní ọjọ́ kan nípamọ́fún gbogbo agbéraga àti ọlọ́kàn gíganítorí gbogbo àwọn tí a gbéga (ni a ó rẹ̀sílẹ̀),

13. nítorí gbogbo igi kedari Lẹ́bánónì, tó ga tó rìpóàti gbogbo óákù Báṣánì,

14. nítorí gbogbo òkè gíga ńlá ńláàti àwọn òkè kéé kèè kéé,

15. fún ilé ìṣọ́ gíga gígaàti àwọn odi ìdáàbòbò,

16. fún gbogbo ọkọ̀ àwọn oníṣòwòàwọn ọkọ̀ tí a ṣe lọ́ṣọ̀ọ́.

17. Ìgbéraga ènìyàn ni a ó tẹ̀ lórí baa ó sì rẹ ìgbéraga ènìyàn sílẹ̀, Olúwa nìkan ṣoṣo ni a ó gbéga ní ọjọ́ náà,

Ka pipe ipin Àìsáyà 2