Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 19:1-4 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ọ̀rọ̀ ìmọ̀ tí ó kan Éjíbítì:Kíyèsíi, Olúwa gun àwọsánmọ̀ tí ó yára lẹ́sinó sì ń bọ̀ wá sí Éjíbítì.Àwọn ère òrìṣà Éjíbítì wárìrì níwájúu rẹ̀,ọkàn àwọn ará Éjíbítì sì ti domi nínú un wọn.

2. “Èmi yóò rú àwọn ará Éjíbítì sókè sí ara wọnarákùnrin yóò bá arákùnrin rẹ̀ jà,aládúgbò yóò dìde sí aládúgbò rẹ̀,ìlú yóò dìde sí ìlú,ilẹ̀ ọba sí ilẹ̀ ọba.

3. Àwọn ará Éjíbítì yóò sọ ìrètí nù,èmi yóò sì sọ èrò wọn gbogbo di òfo;wọn yóò bá àwọn òrìṣà àti ẹ̀mí àwọn òkú sọ̀rọ̀,àwọn awoṣẹ́ àti àwọn abókúsọ̀rọ̀.

4. Èmi yóò fi Éjíbítì lé agbáraàwọn ìkà amúnisìn lọ́wọ́,ọba aláìláàánú ni yóò jọba lé wọn lórí,”ni Olúwa, Olúwa Alágbára wí.

Ka pipe ipin Àìsáyà 19