Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 13:12-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

12. Èmi yóò jẹ́ kí ọkùnrin kí ó wọnju ojúlówóo wúrà lọ,yóò sì ṣọ̀wọ́n ju wúrà ófírì lọ.

13. Nítorí náà èmi yóò jẹ́ kí àwọn ọ̀run kí ó wárìrì;ayé yóò sì mì tìtì ní ibùjókòó rẹ̀láti ọwọ́ ìbínú Olúwa àwọn ọmọ-ogun,ní ọjọ́ ìbínú gbígbóná an rẹ.

14. Gẹ́gẹ́ bí èkùlù tí à ń dọdẹ rẹ̀,gẹ́gẹ́ bí àgùntàn tí kò ní olùṣọ́,ọ̀kọ̀ọ̀kan yóò padà tọ àwọn ènìyàn rẹ̀ lọ,ọ̀kọ̀ọ̀kan yóò sá padà sí ilẹ̀ abínibí i rẹ̀.

15. Ẹnikẹ́ni tí a bá gbámú ni a ó wọ́ nílẹ̀ tuurutu,gbogbo àwọn tí ọwọ́ bá tẹ̀ ni yóò ti ipa idà kú.

16. Àwọn mọ̀jèsín wọn ni a ó fọ́ sí wẹ́wẹ́ níṣojú wọn,gbogbo ilẹ̀ wọn ni a ó kóàwọn aya wọn ni a ó sì bá dàpọ̀.

17. Kíyèsí i, èmi yóò ru àwọn Mẹ́dísì sókè sí wọn,àwọn tí kò bìkítà fún fàdákàtí kò sì ní inú dídùn sí wúrà.

18. Ọrùn wọn yóò ré àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin lulẹ̀;wọn kò ní ṣàánú àwọn mọ̀jèsíntàbí kí wọn síjú àánú wo àwọn ọmọdé.

Ka pipe ipin Àìsáyà 13