Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 10:1-4 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ègbé ni fún àwọn ti ń ṣe òfin àìṣòdodo

2. láti dún àwọn aláìní ní ẹ̀tọ́ wọnàti láti fa ọwọ́ ìdájọ́ sẹ́yìn kúròníwájú àwọn olùpọ́njú ènìyàn mi,wọ́n sọ àwọn ọ̀pọ̀ di ìjẹ fún wọn.Wọ́n sì ń ja àwọn aláìní lólè.

3. Kí ni ìwọ yóò ṣe ní ọjọ́ ìṣirònígbà tí ìparun bá ti ọ̀nà jínjìn wá?Ta ni ìwọ yóò sá tọ̀ fún ìrànlọ́wọ́?Níbo ni ìwọ yóò fi ọrọ̀ rẹ sí?

4. Ohunkóhun kò ní ṣẹ́kù mọ́ bí kò ṣe láti tẹ̀ ba láàrin àwọn ìgbèkùntàbí kí o ṣubú sáàrin àwọn tí a pa.Pẹ̀lú gbogbo nǹkan wọ̀nyí, ìbínú rẹ̀ kò kúrò,ọwọ́ rẹ̀ sì tún gbé sókè.

Ka pipe ipin Àìsáyà 10